Kí Ni Mo Gbọ́dọ̀ Ṣe Kí N Baà Le Là? — Ìṣàmúlò Rẹ̀ Ní Ọ̀nà Àṣepàtàkì · Ìwé Mímọ́ KJV Pẹ̀lú Àwọn Nọ́mbà Strong — Ìdánwò Bíbélì
Ìdánwò Bíbélì
Kí Ni Mo Gbọ́dọ̀ Ṣe Kí N Baà Le Là? — Ìṣàmúlò Rẹ̀ Ní Ọ̀nà Àṣepàtàkì · Ìwé Mímọ́ KJV Pẹ̀lú Àwọn Nọ́mbà Strong — Ìdánwò Bíbélì
Fún ìtọ́kasí kọ̀ọ̀kan nísàlẹ̀, yan ohun tí ẹsẹ náà kọ́ni. Ìwọ̀n rẹ yóò farahàn ní ìparí.
Èyí ni àdánwò tí a ń ṣàyẹ̀wò. Kọjá rẹ̀ láti jèrè ẹ̀san sí Ẹ̀rí-ìjẹ́rìí Ìfọwọ́sí Iṣẹ́-Ìsìn rẹ.
Romu 6:17 — Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run pé, bí ẹ̀yin ti jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ rí, ẹ̀yin jẹ́ olùgbọ́ran láti ọkàn wá sí àpẹẹrẹ ________ èyí tí Ọlọ́run fi lé yín lọ́wọ́.
àdúrà
ahọ́n
ẹ̀kọ́
Jakọbu 1:18 — Ó pinnu láti fi ọ̀rọ̀ òtítọ́ bí wa kí àwa kí ó le jẹ́ ________ nínú ohun gbogbo tí ó dá.
ìjọ
gbòǹgbò
àkọ́so
1 Peteru 1:23 — Bí a ti tún yín bí, kì í ṣe láti inú ________ wá, bí kò ṣe èyí ti kì í díbàjẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ń bẹ láààyè tí ó sì dúró.
ìdíbàjẹ́
ìtẹ́wọ́gbà
aláìgbàgbọ́
Romu 8:15 — Nítorí ẹ̀yin kò tún gba ẹ̀mí ẹrú láti máa bẹ̀rù mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gba ẹ̀mí ________, nípa èyí tí àwa fi ń ké pé “Ábbà, Baba.”
ìyànfẹ́
ìsọdọmọ
àìwà-bí-Ọlọ́run
Ìṣe àwọn Aposteli 8:12 — Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n gba Filipi gbọ́ bí ó ti ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run, àti orúkọ Jesu Kristi, a ________ wọn.
gbàgbọ́
bamitiisi
láradá
Ìṣe àwọn Aposteli 10:47 — “Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má ________ àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?”
gbàgbọ́
bamitiisi
wàásù
Romu 6:11 — Nítorí náà, ẹ ka ara yín bí òkú sí ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n bí ________ sí Ọlọ́run nínú Kristi Jesu.
olódodo
alààyè
ìlérí
Luku 8:15 — Ṣùgbọ́n ti ilẹ̀ rere ni àwọn tí wọ́n fi ọkàn òtítọ́ àti rere gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, wọ́n dìímú ṣinṣin, wọ́n sì fi ________ so èso.
sùúrù
ẹ̀rí
líle
Saamu 1:2 — Ṣùgbọ́n ayọ̀ inú rẹ̀ wà nínú òfin Olúwa àti nínú òfin rẹ̀ ni ó ń ṣe àṣàrò ní ________ àti òru.
kìnnìún
ọ̀sán
kedari
Joṣua 1:8 — Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ________ àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
ọ̀sán
ìṣọ́
awọ
1 Johanu 1:7 — Ṣùgbọ́n bí àwa bá ń rìn nínú ìmọ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òun ti ń wà nínú ìmọ́lẹ̀, àwa ní ________ pẹ̀lú ara wa, àti pé ẹ̀jẹ̀ Jesu Kristi, Ọmọ rẹ̀, wẹ̀ wá nù kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo.
ìdàpọ̀
ṣẹ́gun
jẹ́rìí
2 Peteru 3:18 — Ṣùgbọ́n ẹ máa dàgbà nínú oore-ọ̀fẹ́ àti nínú ìmọ̀ Olúwa àti ________ wa Jesu Kristi. Ẹni tí ògo wà fún nísinsin yìí àti títí láé! Àmín.
Amaleki
Kohati
Olùgbàlà
Romu 13:11 — Àti èyí, bí ẹ̀yin ti mọ àkókò pé, ó ti tó wákàtí nísinsin yìí fún yín láti jí lójú orun, nítorí nísinsin yìí ni ________ wa súnmọ́ etílé ju ìgbà tí àwa ti gbàgbọ́ lọ.
ayọ̀
ìgbàlà
ẹ̀kọ́
1 Peteru 5:8 — Ẹ máa wà ni àìrékọjá, ẹ máa ṣọ́ra; nítorí èṣù ________ yín, bí i kìnnìún tí ń ké ramúramù, ó ń rìn káàkiri, ó ń wa ẹni tí yóò pajẹ.
àgbélébùú
ọ̀tá
àyànfẹ́
Romu 1:16 — Èmi kò tijú ________ Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú.
ìgbàgbọ́
ìyìnrere
ìlérí
Eksodu 14:13 — Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ________ kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
ẹrú
ṣinṣin
ìbú
Heberu 10:38 — Ṣùgbọ́n, “________ ni yóò yè nípa ìgbàgbọ́. Ṣùgbọ́n bí o ba fàsẹ́yìn, ọkàn mi kò ní inú dídùn sí i.”
tẹríba
oore-ọ̀fẹ́
Olódodo
Luku 14:28 — “Nítorí ta ni nínú yín tí ń pète láti kọ́ ilé ________, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó kí ó ṣírò iye owó rẹ̀, bí òun ní tó tí yóò fi parí rẹ̀.
ìṣọ́
panṣágà
wàásù
Ìfihàn 12:11 — Wọ́n sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ nítorí ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn náà, àti nítorí ọ̀rọ̀ ________ wọn, wọn kò sì fẹ́ràn ẹ̀mí wọn àní títí dé ikú.
òkúta
ẹ̀rí
òtítọ́
Jakọbu 1:12 — Ìbùkún ni fún ọkùnrin tí ó fi ọkàn rán ìdánwò; nítorí nígbà tí ó bá yege, yóò gba ________ ìyè, tí Olúwa ti ṣèlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ.
ẹyẹ
ìṣúra
adé
Ìfihàn 7:9 — Lẹ́yìn náà, mo ri, sì kíyèsi i, ________ ènìyàn tí ẹnikẹ́ni kò lè kà, láti inú orílẹ̀-èdè gbogbo, àti ẹ̀yà, àti ènìyàn, àti láti inú èdè gbogbo wá, wọn dúró níwájú ìtẹ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà, a wọ̀ wọ́n ni aṣọ funfun, imọ̀ ọ̀pẹ si ń bẹ ni ọwọ́ wọn.
ọ̀pọ̀lọpọ̀
odò
odi
1 Peteru 1:5 — ẹyin tí a ń pamọ́ nípa agbára Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ si ________, tí a múra láti fihàn ní ìgbà ìkẹyìn.
ìgbàlà
ayọ̀
ẹ̀rí
Juda 1:24 — Ǹjẹ́ mo fi yín lé ẹni tí o lè pa yín mọ́ kúrò nínú ìkọ̀sẹ̀, tí o sì lè mú yín wá síwájú ògo rẹ̀ láìlábùkù pẹ̀lú ________ ńlá lọ́wọ́—