🌐 Language
'Olelo Hawai'iAfaan Oromoobahasa IndonesiaBelarusianBrezhonegCebuanoChamorroChichewachiShonaChongthuCiyawoDanskDeutschEestiEnglishEspañolEsperantoeʋegbeFrançaisHausaHrvatskiIgboIlocanoItalianoKikuyuKiswahiliKiyombiKreyòl AyisyenLatinaLatviešulietuviųLingálaLugandaMagyarMahasuiMāoriNederlandsNorskPohnpeianPolskiPortuguêsQach’abelRomaniRomânăSanskritSetswanaShqipsrpski jezikSuomiSvenskaTagalogTiếng ViệtTonganTwiTürkçeUyghur tiliYorùbáÍslenskaČeštinaБългарскиРусскийУкраїнськаעבריתاردوالعربيةفارسیكوردی سۆرانیअहिराणी‎नेपालीभद्रवाही‎मराठीमानक हिन्दी‎हरियाणवी‎অসমীয়াবাংলাਪੰਜਾਬੀગુજરાતીଓଡ଼ିଆ‎தமிழ்తెలుగుಕನ್ನಡമലയാളംไทยဗမာἙλληνική中文日本語한국어+ Gbogbo Èdè
See More Jesus
Yorùbá

Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Àánú? — Gbígbé E Yè · Àwọn Ìwé Mímọ́ KJV pẹ̀lú Àwọn Nọ́mbà Strong — Ìdánwò Bíbélì

Ìdánwò Bíbélì

Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Àánú? — Gbígbé E Yè · Àwọn Ìwé Mímọ́ KJV pẹ̀lú Àwọn Nọ́mbà Strong — Ìdánwò Bíbélì

Fún ìtọ́kasí kọ̀ọ̀kan nísàlẹ̀, yan ohun tí ẹsẹ náà kọ́ni. Ìwọ̀n rẹ yóò farahàn ní ìparí.

Èyí ni àdánwò tí a ń ṣàyẹ̀wò. Kọjá rẹ̀ láti jèrè ẹ̀san sí Ẹ̀rí-ìjẹ́rìí Ìfọwọ́sí Iṣẹ́-Ìsìn rẹ.

Matiu 9:27 — Nígbà tí Jesu sì jáde níbẹ̀, àwọn ọkùnrin ________ méjì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, wọ́n ń kígbe sókè wí pé, “Ṣàánú fún wa, ìwọ ọmọ Dafidi.”
ẹlẹ́rìí
níhìn-ín
afọ́jú
Matiu 15:22 — Obìnrin kan láti Kenaani, tí ó ń gbé ibẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ó ń ________, ó sì kígbe pé, “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi; ọmọbìnrin mi ní ẹ̀mí èṣù ti ń dá a lóró gidigidi.”
bẹ̀bẹ̀
ìrẹ̀lẹ̀
pípé
Isaiah 30:18 — Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. ________ ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
kedari
Ìbùkún
ẹ̀dá
Numeri 6:24 — “‘ “Kí Olúwa ________ un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
bùkún
jogún
ikú
Saamu 145:9 — Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní ________ lórí ohun gbogbo tí ó dá.
ẹ̀ṣẹ̀
ìtẹ́
àánú
Isaiah 49:15 — “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ________ rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
odi
ọmú
ìbáwí
Jeremiah 31:20 — ________ kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Edomu
Benjamini
Efraimu
1 Ọba 3:26 — Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún ________ fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
àánú
májẹ̀mú
ògo
Luku 15:20 — Ó sì dìde, ó sì tọ baba rẹ̀ lọ. “Ṣùgbọ́n nígbà tí ó sì wà ní òkèrè, baba rẹ̀ rí i, ________ ṣe é, ó sì súré, ó rọ̀ mọ́ ọn ní ọrùn, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
àánú
ìtẹ́
májẹ̀mú
1 Ọba 8:23 — Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ________ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
Ramoti
Parani
ìsàlẹ̀
Saamu 89:28 — Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ________ mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
dídùn
èrè
ṣinṣin
Saamu 89:33 — ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ________ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
gbàgbé
ṣinṣin
ẹ̀gàn
Isaiah 54:10 — Bí a tilẹ̀ mi àwọn òkè ńlá tí a sì ṣí àwọn òkè kékeré nídìí, síbẹ̀síbẹ̀ ìfẹ́ àìkùnà mi fún ọ kì yóò yẹ̀ láéláé tàbí májẹ̀mú àlàáfíà ni a ó mú kúrò,” ni Olúwa, ẹni tí ó síjú ________ wò ọ́ wí.
ìtẹ́
ẹ̀ṣẹ̀
àánú
Saamu 25:10 — Gbogbo ipa ________ Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
iṣẹ́
ọ̀nà
ẹbọ
Kolose 3:12 — Nítorí náà, bí àyànfẹ́ Ọlọ́run, ẹni mímọ́ àti olùfẹ́, ẹ gbé ọkàn ìyọ́nú wọ̀, ìṣoore, ________, inú tútù àti sùúrù.
ìtùnú
àìṣòdodo
ìrẹ̀lẹ̀
Filipi 2:1 — Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ________ kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà
ìtùnú
ìgboyà
ìrẹ̀lẹ̀
Romu 12:1 — Nítorí náà mo fi ìyọ́nú Ọlọ́run bẹ̀ yín ará, kí ẹ̀yin kí ó fi ara yín fún Ọlọ́run ní ẹbọ ààyè mímọ́, ________, èyí ni iṣẹ́ ìsìn yín tí ó tọ̀nà.
ìtẹ́wọ́gbà
èrè
ìdíbàjẹ́
Romu 6:13 — Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀yà ara yín kan di ohun èlò ohun búburú, nípa ẹ̀ṣẹ̀ dídá. Ṣùgbọ́n ẹ fi wọn fún Ọlọ́run pátápátá. Wọ́n ti di ààyè, ẹ jẹ́ kí wọn di ohun èlò ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí ó lè lò wọ́n fún àwọn ________ rẹ̀ tí ó dára.
ìlànà
ìpọ́njú
ìlérí
1 Samuẹli 17:47 — Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ________ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
igbó
ọ̀kọ̀
ìròyìn
Nehemiah 4:14 — Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ________ àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
ọlọ́lá
àlùfáà
èlé
Matiu 14:14 — Nígbà ti Jesu gúnlẹ̀, tí ó sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, inú rẹ̀ yọ́ sí wọn, ó sì mú àwọn aláìsàn ________.
lẹ́bi
láradá
ìhòhò
Marku 1:41 — Jesu kún fún ________, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
ìtẹ́
májẹ̀mú
àánú
Luku 7:13 — Nígbà tí Olúwa sì rí i, ________ rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
ìtẹ́
àánú
májẹ̀mú
Jakọbu 5:11 — Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù ________, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
Elijah
Noa
Jobu
Oniwaasu 4:9 — Ẹni méjì sàn ju ẹnìkan, nítorí wọ́n ní ________ rere fún làálàá wọn.
ìmọ̀
èrè
ìbànújẹ́
Jakọbu 5:16 — Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà ________ ń ṣe ní agbára púpọ̀.
ẹlẹ́rìí
olódodo
ìwé
Saamu 100:5 — Nítorí tí Olúwa pọ̀ ní ________ ìfẹ́ rẹ̀ sì wà títí láé; àti òtítọ́ rẹ̀ láti ìran de ìran.
títóbi
ìrántí
oore
Saamu 89:1 — Èmi kọrin ________ ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
ìrántí
títóbi
ẹ̀bẹ̀
Luku 1:50 — Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ________.
ìrandíran
ìkọ̀sẹ̀
àgàbàgebè

← Padà sí ẹ̀kọ́ náà